Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Mátíù 22:36-46 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

36. Ó wí pé, “Olùkọ́ èwo ni ó ga jùlọ nínú àwọn òfin?”

37. Jésù dáhùn pé, “ ‘Fẹ́ Olúwa Ọlọ́run rẹ pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ, gbogbo ẹ̀mí rẹ àti gbogbo inú rẹ.’

38. Èyí ni òfin àkọ́kọ́ àti èyí tí ó tóbi jùlọ.

39. Èkejì tí ó tún dàbí rẹ̀ ní pé, ‘Fẹ́ràn ọmọ ẹni kejì rẹ gẹ́gẹ́ bí ara rẹ.’

40. Lórí àwọn òfin méjèèjì yìí ni gbogbo òfin àti àwọn wòlíì rọ̀ mọ́.”

41. Bí àwọn Farisí ti kó ara wọn jọ, Jésù béèrè lọ́wọ́ wọn pé,

42. “Kí ni ẹ rò nípa Kírísítì? Ọmọ ta ni òun ń ṣe?”Wọ́n dáhùn pé, “Ọmọ Dáfídì.”

43. Ó sì wí fún wọn pé, “Kí ni dé tí Dáfídì, tí ẹ̀mí ń darí, pè é ní ‘Olúwa’? Nítorí ó wí pé,

44. “ ‘Olúwa sọ fún Olúwa mi,“Jòkòó ní ọwọ́ ọ̀tún mitítí tí èmi yóò fi fi àwọn ọ̀ta rẹsí abẹ́ ẹsẹ̀ rẹ.” ’

45. Ǹjẹ́ bí Dáfídì bá pè é ni ‘Olúwa,’ báwo ni òun se lè jẹ́ ọmọ rẹ̀?”

46. Kò sí ẹnì kan tí ó lè sọ ọ̀rọ̀ kan ni ìdáhùn, kò tún sí ẹni tí ó tún bí i léèrè ohun kan mọ́ láti ọjọ́ náà mọ́.

Ka pipe ipin Mátíù 22