Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Mátíù 2:7-11 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

7. Nígbà náà ni Hérọ́dù ọba pe àwọn amòye náà sí ìkọ̀kọ̀, ó sì wádìí ni ọwọ́ wọn, àkókò náà gan-an tí wọ́n kọ́kọ́ rí ìràwọ̀.

8. Ó sì rán wọn lọ sí Bẹ́tílẹ́hẹ́mù, ó sì wí pé, “Ẹ lọ ṣe ìwádìí fínnífínní ní ti ọmọ náà tí a bí. Lẹ́yìn tí ẹ bá sì rí i, ẹ padà wá sọ fún mi, kí èmi náà le lọ foríbalẹ̀ fún un.”

9. Nígbà tí wọ́n sì gbọ́ ọ̀rọ̀ ọba, wọ́n mú ọ̀nà wọn pọ̀n, sì wò ó, ìràwọ̀ tí wọ́n ti rí láti ìhà ìlà-oòrùn wá, ó ṣáájú wọn, títítí ó fi dúró lókè ibi tí ọmọ náà gbé wà.

10. Nígbà tí wọ́n sì rí ìràwọ̀ náà, ayọ̀ kún ọkàn wọn.

11. Bí wọ́n tí wọ inú ilé náà, wọn rí ọmọ ọwọ́ náà pẹ̀lú Màríà ìyá rẹ̀, wọ́n wólẹ̀, wọ́n forí balẹ̀ fún un. Nígbà náà ni wọ́n tú ẹrù wọn, wọ́n sì ta Jésù lọ́rẹ: wúrà, tùràrí àti òjíà.

Ka pipe ipin Mátíù 2