Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Mátíù 17:8-22 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

8. Nígbà tí wọ́n sì gbé ojú wọn sókè, tí wọ́n sì wò ó, Jésù nìkan ni wọn rí.

9. Bí wọ́n sì ti ń sọ̀ kalẹ̀ láti orí òkè, Jésù pàṣẹ fún wọn pé “Ẹ kò gbọdọ̀ sọ fún ẹnikẹ́ni ohun tí ẹ rí, títí ọmọ-ènìyàn yóò fi jí dìde kúrò nínú òkú”

10. Àwọn ọmọ-ẹ̀yin rẹ̀ béèrè lọ́wọ́ rẹ́ pé, “Kí ni ó fà á tí àwọn olùkọ́ òfin fi ń wí pé, Èlíjà ní láti kọ́ padà wá”

11. Jésù sì dáhùn pé, “Dájúdájú òtítọ́ ni wọ́n ń sọ. Èlíjà wá láti fi gbogbo nǹkan sí ipò.

12. Ṣùgbọ́n èmi wí fún yín lóòótọ́; Èlíjà ti dé. Ṣùgbọ́n wọn kò mọ̀ ọ́n, ọ̀pọ̀ tilẹ̀ hu ìwà búburú sí i. Bákan náà, Ọmọ ènìyàn náà yóò jìyà lọ́wọ́ wọn pẹ̀lú.”

13. Nígbà náà, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn mọ̀ pé ó n sọ̀rọ̀ nípa Jòhánù onítẹ̀bọmi fún wọn ni.

14. Nígbà tí wọ́n sì dé ọ̀dọ̀ ìjọ ènìyàn,. ọkùnrin kan tọ̀ Jésù wá, ó sì wólẹ̀ níwájú rẹ̀, ó wí pé,

15. “Olúwa, ṣàánú fún ọmọ mi, nítorí tí ó ní wárápá. Ó sì ń joró gidigidi, nígbà púpọ̀ ni ó máa ń ṣubu sínú iná tàbí sínú omi.

16. Mo sì ti mú un tọ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ, ṣùgbọ́n wọn kò lè wò ó sàn.”

17. Jésù sì dáhùn wí pé, “A! ẹ̀yìn alágídí ọkàn àti aláìgbàgbọ́ ènìyàn, èmi yóò ti bá yín gbé pẹ́ tó? Èmi ó sì ti fara dà á fún yín tó? Ẹ mú un wá sọ́dọ̀ mi níhìn-ín yìí.”

18. Nígbà náà ni Jésù bá ẹ̀mí èṣù tí ó ń bẹ nínú ọmọkùnrin náà wí, ó sì fi í sílẹ̀, à mú ọmọkùnrin náà láradá láti ìgbà náà lọ.

19. Lẹ́yìn èyí, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ sì bi Jésù níkọ̀kọ̀ pé, “È é ṣe tí àwa kò lè lé ẹ̀mí èṣù náà jáde?”

20. Jésù sọ fún wọn pé, “Nítorí ìgbàgbọ́ yín kéré. Lóòòtọ́ ni mo wí fún yin, bí ẹ bá ni ìgbàgbọ́, bí ó tilẹ̀ kéré bí músítadì, ẹ̀yin lè wí fún òkè yìí pé, ‘Ṣípò kúrò níhìn-ín yìí’ òun yóò sì sí ipò. Kò sì nií sí ohun tí kò níí ṣe é ṣe fún yín.”

21. Ṣùgbọ́n irú ẹ̀mí èṣù yìí kò ní lọ, bí kò ṣe nípa ààwẹ̀ àti àdúrà.

22. Nígbà tí wọ́n sì ti wà ní Gálílì, Jésù sọ fún wọn pé, “Láìpẹ́ yìí a ó fi Ọmọ ènìyàn lé àwọn ènìyàn lọ́wọ́.

Ka pipe ipin Mátíù 17