Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Mátíù 17:10-19 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

10. Àwọn ọmọ-ẹ̀yin rẹ̀ béèrè lọ́wọ́ rẹ́ pé, “Kí ni ó fà á tí àwọn olùkọ́ òfin fi ń wí pé, Èlíjà ní láti kọ́ padà wá”

11. Jésù sì dáhùn pé, “Dájúdájú òtítọ́ ni wọ́n ń sọ. Èlíjà wá láti fi gbogbo nǹkan sí ipò.

12. Ṣùgbọ́n èmi wí fún yín lóòótọ́; Èlíjà ti dé. Ṣùgbọ́n wọn kò mọ̀ ọ́n, ọ̀pọ̀ tilẹ̀ hu ìwà búburú sí i. Bákan náà, Ọmọ ènìyàn náà yóò jìyà lọ́wọ́ wọn pẹ̀lú.”

13. Nígbà náà, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn mọ̀ pé ó n sọ̀rọ̀ nípa Jòhánù onítẹ̀bọmi fún wọn ni.

14. Nígbà tí wọ́n sì dé ọ̀dọ̀ ìjọ ènìyàn,. ọkùnrin kan tọ̀ Jésù wá, ó sì wólẹ̀ níwájú rẹ̀, ó wí pé,

15. “Olúwa, ṣàánú fún ọmọ mi, nítorí tí ó ní wárápá. Ó sì ń joró gidigidi, nígbà púpọ̀ ni ó máa ń ṣubu sínú iná tàbí sínú omi.

16. Mo sì ti mú un tọ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ, ṣùgbọ́n wọn kò lè wò ó sàn.”

17. Jésù sì dáhùn wí pé, “A! ẹ̀yìn alágídí ọkàn àti aláìgbàgbọ́ ènìyàn, èmi yóò ti bá yín gbé pẹ́ tó? Èmi ó sì ti fara dà á fún yín tó? Ẹ mú un wá sọ́dọ̀ mi níhìn-ín yìí.”

18. Nígbà náà ni Jésù bá ẹ̀mí èṣù tí ó ń bẹ nínú ọmọkùnrin náà wí, ó sì fi í sílẹ̀, à mú ọmọkùnrin náà láradá láti ìgbà náà lọ.

19. Lẹ́yìn èyí, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ sì bi Jésù níkọ̀kọ̀ pé, “È é ṣe tí àwa kò lè lé ẹ̀mí èṣù náà jáde?”

Ka pipe ipin Mátíù 17