Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Mátíù 14:1-11 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ní àkókò náà ni Hẹ́rọ́dù ọba Tẹ́tírákì gbọ́ nípa òkìkí Jésù,

2. ó wí fún àwọn ọmọ-ọ̀dọ̀ rẹ̀ pé, “Dájúdájú Jòhánù onítẹ́bọmi ni èyí, ó jíǹde kúrò nínú òkú. Ìdí nìyí tí ó fi ní agbára láti ṣiṣẹ́ ìyanu wọ̀nyí.”

3. Nísìnsin yìí Hẹ́rọ́dù ti mú Jòhánù, ó fi ẹ̀wọ̀n dè é, ó sì fi sínú túbú, nítorí Hẹ́rọ́díà aya Fílípì arákùnrin rẹ̀,

4. nítorí Jòhánù onítẹ̀bọmi ti sọ fún Hẹ́rọ́dù pé, “Kò yẹ fún ọ láti fẹ́ obìnrin náà.”

5. Hẹ́rọ́dù fẹ pa Jòhánù, ṣùgbọ́n ó bẹ̀rù àwọn ènìyàn nítorí gbogbo ènìyàn gbàgbọ́ pé wòlíì ni.

6. Ní ọjọ́ àsè ìrántí ọjọ́ ìbí Hẹ́rọ́dù, ọmọ Hẹ́rọ́díà obìnrin jó dáadáa, ó sì tẹ́ Hẹ́rọ́dù lọ́run gidigidi.

7. Nítorí náà, Hẹ́rọ́dù jẹ́ ẹ̀jẹ́ láti fún un ní ohunkóhun ti ó bá béèrè fún.

8. Pẹ̀lú ìmọ̀ràn láti ọ̀dọ̀ ìyá rẹ̀, ó béèrè pé, “Fún mi ni orí Jòhánù onítẹ̀bọmi nínú àwo pọ̀kọ́”.

9. Inú ọba bàjẹ́ gidigidi, ṣùgbọ́n nítorí ẹ̀jẹ́ rẹ̀ àti kí ojú má ba à tì í níwájú àwọn àlejò tó wà ba jẹ àsè, ó pàṣẹ pé kí wọ́n fún un gẹ́gẹ́ bí o ti fẹ́.

10. Nítorí náà, a bẹ́ orí Jòhánù onítẹ̀bọmi nínú ilé túbú.

11. A sì gbé orí rẹ̀ jáde láti fi fún ọmọbìnrin náà nínú àwo pọ̀kọ́, òun sì gbà á, ó gbé etọ ìyá rẹ̀ lọ.

Ka pipe ipin Mátíù 14