Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Máàkù 6:12-19 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

12. Wọ́n jáde lọ láti wàásù ìrònúpìwàdà fún àwọn ènìyàn.

13. Wọ́n lé ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ẹ̀mí àìmọ́ jáde. Wọ́n sì ń fi òróró kun orí àwọn tí ara wọn kò dá, wọ́n sì mú wọn láradá.

14. Láìpẹ́, ọba Hẹ́rọ́dù gbọ́ nípa Jésù, nítorí níbi gbogbo ni a ti ń sọ̀rọ̀ iṣẹ́ ìyanu rẹ̀. Ọba náà rò pé, “Jòhánù Onítẹ́bọ́mì jínde kúrò nínú òkú, nítorí náà ni iṣẹ́ ìyanu ṣe ń ṣe láti ọwọ́ rẹ”

15. Àwọn mìíràn wí pé, “Èlíjà ní.”Àwọn mìíràn wí pé, “Wòlíì bí ọ̀kan lára àwọn àtijọ́ tó ti kú ló tún padà sáyé.”

16. Ṣùgbọ́n nígbà tí Hẹ́rọ́dù gbọ́ èyí, ó wí pé “Jòhánù tí mo tí bẹ́ lórí ni ó ti jíǹde kúrò nínú òkú.”

17. Hẹ́rọ́dù tikararẹ́ sá ti ránṣẹ mú Johanu, tìkaararẹ̀ sínu túbú nítorí Hẹrodíà aya Fílípì arákùnrin rẹ̀ nítorí tí ó fi ṣe aya.

18. Nítorí tí ó tẹnumọ́ ọn wí pé, “Kò tọ́ sí ọ láti fi ìyàwó arákùnrin rẹ ṣe aya.”

19. Nítorí náà ni Hẹ́rọ́díà ṣe ní ìn sínú, òun sì fẹ́ pa á, ṣùgbọ́n kò le se é.

Ka pipe ipin Máàkù 6