Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Máàkù 3:1-5 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Nígbà tí Jésù wá sí sínágọ́gù. Sì kíyèsí i ọkùnrin kan wà níbẹ̀, tí ọwọ́ rẹ̀ kan rọ.

2. Àwọ́n kan nínú wọn sì ń wa ọ̀nà láti fi ẹ̀sùn kan Jésù, ítorí náà, wọn ń sọ Ọ́ bí yóò u un láradá ní ọjọ́ ìsinmi.

3. Jésù wí fún ọkùnrin tí ọwọ́ rẹ̀ rọ náà pé, “Dìde dúró ní iwájú ìjọ ènìyàn.”

4. Nígbà náà ni Jésù bèèrè lọ́wọ́ wọ́n pé, “Ǹjẹ́ ó bá òfin mu ní ọjọ́ ìsinmi bóyá láti ṣe rere, tàbí láti ṣe búburú! Láti gbà ẹ̀mí là, tàbí pa á run?” Ṣùgbọ́n wọ́n dákẹ́ láìfèsì.

5. Nígbà tí ó sì wo gbogbo wọn yíká pẹ̀lú ìbínú, ọkàn rẹ̀ sì bàjẹ́ nítorí líle àyà wọn, ó sọ fún ọkùnrin náà pé, “Na ọwọ́ rẹ jáde.” Ó nà án jáde, ọwọ́ náà sì bọ̀ sípò padà pátápátá.

Ka pipe ipin Máàkù 3