Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Máàkù 14:18-27 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

18. Bí wọ́n sì ti jókòó yí tábìlì ká, tí wọ́n ń jẹun, Jésù wí pé, “Lóòtọ́ ni mo wí fún un yín, ọ̀kan nínú ẹ̀yin tí ẹ ń bá mi jẹun yìí ni yóò fí mí hàn.”

19. Ọkàn wọn sì bẹ̀rẹ̀ sí í dàrú. Olúkúlùkù sì ń bi í ní ọkọ̀ọ̀kan wí pé, “Dájúdájú, kì í ṣe èmi?”

20. Ó sì dáhùn wí pé, “Ọ̀kan nínú ẹ̀yin méjìlá tí ó ń bá mi jẹun nísinsin yìí ni.

21. Ní tòótọ́ Ọmọ-Ènìyàn ń lọ bí a ti kọ̀wé nípa rẹ̀: Ṣùgbọ́n ègbé ní fún ọkùnrin náà, láti ọwọ́ ẹni tí a ti fi Ọmọ-Ènìyàn hàn. Ìbá sàn fún un bí a kò bá bí i rárá.”

22. Bí wọ́n ti ń jẹun lọ́wọ́, Jésù mú ìṣù àkàrà kan, ó gbàdúrà sí i. Lẹ́yìn náà ó bù ú sí wẹ́wẹ́, ó sì fi fún wọn. Ó wí pé “Ẹ gbà jẹ, èyí yìí ni ara mi.”

23. Ó sì tún gbé ago wáìnì, ó gbàdúrà ọpẹ́ sí Ọlọ́run. Ó sì gbé e fún wọn. Gbogbo wọn sì mu nínú rẹ̀.

24. Ó sì wí fún wọn pé, “Èyí ni ẹ̀jẹ̀ mi ti májẹ̀mú túntún, tí a ta sílẹ̀ fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn.

25. Lóótọ̀ ni mo wí fún un yín, èmi kò tún ní mu wáìnì mọ́ títí yóò fi di ọjọ́ náà tí Èmi yóò mu ún ní titun nínú ìjọba Ọlọ́run.”

26. Lẹ́yìn náà wọ́n kọ orin, wọ́n sì gun orí òkè ólífì lọ.

27. Jésù sì wí fún wọn pé, “Gbogbo yín ni ẹ ń bọ̀ wá kosẹ̀ lára mi ni oru òní, a ti kọ̀wé rẹ pé:“ ‘Èmi yóò lu olùsọ́-àgùntànàwọn agbo àgùntàn yóò sì fọ́nká.’

Ka pipe ipin Máàkù 14