Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Máàkù 14:1-3 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Lẹ́yìn ọjọ́ méjì ni Àjọ ìrékọjá àti àjọ tí wọ́n ń fi àkàrà àìwú se ku ọ̀túnla. Àwọn olórí àlùfáà àti àwọn olùkọ́-òfin sì ń wá ọ̀nà láti mú Jésù ní ìkọ̀kọ̀, kí wọn sì pa á.

2. Ṣùgbọ́n wọ́n wí pé, “A kò ní mú un ní ọjọ́ Àjọ, kí àwọn ènìyàn má bá á fa ìjàngbọ̀n.”

3. Nígbà tí ó sì wà ní Bẹ́tanì ni ilé Símónì adẹ́tẹ̀ bí ó ti jókòó ti oúnjẹ, obìnrin kan wọlé, ti òun ti ìgò òróró ìpara olówó iyebíye, ó sí ìgò náà, ó sì da òróró náà lé Jésù lórí.

Ka pipe ipin Máàkù 14