Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Máàkù 12:30-38 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

30. Kí ìwọ kí ó fi gbogbo àyà rẹ, àti gbogbo ọkàn rẹ, àti gbogbo ẹ̀mí rẹ, àti gbogbo agbára rẹ fẹ́ Olúwa Ọlọ́run rẹ, èyí ní òfin kìn-ín-ní.’

31. Èkejì ni pé: ‘Fẹ ọmọnikejì rẹ.’ Kò sí òfin mìíràn tó ga ju méjèèjì yìí lọ.”

32. Olùkọ́ ófin náà dáhùn pé, “Olùkọ́, ìwọ sọ òtítọ́ nípa pé Ọlọ́run kan ní ó ń bẹ, àti pé kò sí òmíràn àfi òun nìkan.

33. Àti pé, mo mọ bí ó ti ṣe pàtàkì tó láti fẹ́ ẹ pẹ̀lú gbogbo agbára mi, àti pẹ̀lú pé kí n fẹ́ràn ọmọnìkéjì mi gẹ́gẹ́ bí ara mi, ju kí n rú oríṣiiríṣii ẹbọ lórí i pẹpẹ ilé ìsìn.”

34. Jésù rí i dájú pé òye ọkùnrin yìí ga, nítorí náà, Jésù sọ fún un pé, “Arákùnrin, ìwọ kò jìnà sí à ti dé ìjọba Ọ̀run.” Láti ìgbà náà lọ, ẹnikẹ́ni kò tún béèrè ohun kan lọ́wọ́ Jésù.

35. Lẹ́yìn náà, nígbà tí Jésù ń kọ́ àwọn Ọmọ-Ènìyàn nínú tẹ́ḿpílì, ó béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “È é ṣe tí àwọn olùkọ́-òfin fi gbà wí pé Kírísítì náà ní láti jẹ́ ọmọ Dáfídì?

36. Nítorí tí Dáfídì tìkárarẹ̀, ti ń ti ipa Ẹ̀mí Mímọ́ sọ̀rọ̀ wí pé:“ ‘Ọlọ́run sọ fún Olúwa mi:“Jókòó ní ọwọ́ ọ̀tún mi,títí èmi yóò fi sọ àwọn ọ̀ta rẹdi àpótí ìtìṣẹ̀ rẹ.” ’

37. Níwọ̀n ìgbà tí Dáfídì tìkáraarẹ̀ pè é ní ‘Olúwa,’ Báwo ni ó tún ṣe lè jẹ́ ọmọ rẹ̀?”Ọ̀pọ̀ ènìyàn sì fi ayọ̀ gbọ ọ̀rọ̀ rẹ̀.

38. Ó sì wí fún wọn pé nínú ẹ̀kọ́ rẹ̀ pé, “Ẹ sọ́ra lọ́dọ̀ àwọn olùkọ́-òfin tí wọ́n fẹ́ láti máa wọ aṣọ gígun rìn kiri, tí wọ́n sì fẹ́ ìkíni ní ọja,

Ka pipe ipin Máàkù 12