Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Máàkù 11:29-33 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

29. Jésù dá wọn lóhùn pé, “Èmi yóò sọ fún un yín bí ẹ bá lè dáhùn ìbéèrè mi yìí.”

30. Ìtẹ̀bọmi Jòhánù láti ọ̀run wa ni, tàbí láti ọ̀dọ̀ ènìyàn? “Ẹ dá mi lóhùn!”

31. Wọ́n bá ara wọn jíjòrò pé: “Bí a bá wí pé Ọlọ́run ni ó rán an wá nígbà náà yóò wí pé, ‘nígbà tí ẹ mọ̀ bẹ́ẹ̀, èéṣe tí ẹ kò fi gbà à gbọ?’

32. Ṣùgbọ́n bí a bá sọ wí pé Ọlọ́run kọ́ ló rán an, nígbà náà àwọn ènìyàn yóò bẹ̀rẹ̀ rògbòdìyàn. Nítorí pé gbogbo ènìyàn ló gbàgbọ́ pé wòlíì gidi ni Jòhánù.”

33. Nítorí náà, Wọ́n kọjú sí Jésù wọn sì dáhùn pé, “Àwa kò mọ̀.”Nígbà náà ni Jésù wí pé, “Níwọ̀n ìgbà tí ẹ kò lè dáhùn ìbéèrè mi, Èmi náà kì yóò sọ fún yín àṣẹ tí mo fi ń ṣe nǹkan wọ̀nyí.”

Ka pipe ipin Máàkù 11