Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Máàkù 11:25-30 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

25. nígbà tí ẹ bá ń gbàdúrà, ẹ kọ́kọ́ dáríjì ẹni tí ó ṣẹ̀ yín. Baba yín lọ́run yóò dárí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ tiyín náà jì yín.”

26. Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin kò bá dáríjì, Baba yín ti ń bẹ ni ọ̀run kí yóò dárí ẹ̀ṣẹ̀ yín jì yín

27. Lẹ́yìn èyí, wọ́n tún padà sí Jerúsálémù.Bí Jésù ti ń rìn kíri ni tẹ́ḿpílì, àwọn olórí àlùfáà àti àwọn tí ń kọ́ni ni òfin pẹ̀lú àwọn àgbààgbà Júù wá sọ́dọ̀ rẹ̀.

28. Wọ́n béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Àṣẹ wo ni ó fi ń se nǹkan yìí? Ta ni ó sì fún ọ ni àṣẹ yìí láti máa ṣe nǹkan wọ̀nyìí?”

29. Jésù dá wọn lóhùn pé, “Èmi yóò sọ fún un yín bí ẹ bá lè dáhùn ìbéèrè mi yìí.”

30. Ìtẹ̀bọmi Jòhánù láti ọ̀run wa ni, tàbí láti ọ̀dọ̀ ènìyàn? “Ẹ dá mi lóhùn!”

Ka pipe ipin Máàkù 11