Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Máàkù 1:38-45 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

38. Jésù sì dáhùn wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a lọ sí àwọn ìlú mìíràn, kí ń lè wàásù níbẹ̀ pẹ̀lú. Nítorí èyí ni èmi sá à ṣe wá.”

39. Nítorí náà, ó ń kiri gbogbo agbégbé Gálílì, ó ń wàásù nínú àwọn sínágọ́gù. Ó sì ń lé àwọn ẹ̀mí àìmọ́ jáde.

40. Ọkùnrin adẹ́tẹ̀ kan tọ̀ ọ́ wá, ó sì kúnlẹ̀ níwájú rẹ̀. Ó sì bẹ̀bẹ̀ fún ìmúláradà. Ó wí pé, “Bí ìwọ bá fẹ́, ìwọ lè mú mi láradá.”

41. Jésù kún fún àánú, ó na ọwọ́ rẹ̀, ó fi ọwọ́ rẹ̀ bà a, ó wí pé, “Èmí fẹ́. Di mímọ́.”

42. Lójúkan-náà ẹ̀tẹ̀ náà fi sílẹ̀ lọ, ọkùnrin náà sì rí ìwòsàn.

43. Jésù sì kìlọ̀ fún un gidigidi

44. Ó wí pé, “Lọ fi ara rẹ̀ hàn àlùfáà Júù fún àyẹ̀wò. Ṣùgbọ́n má ṣe dúró sọ ohunkóhun fún ẹnikẹ́ni ní ọ̀nà. Mú ẹ̀bùn lọ́wọ́, èyí tí Mósè pa láṣẹ fún adẹ́tẹ̀ tí a múláradá. Èyí tí í ṣe ẹ̀rí pé, ó ti rí ìwòsàn.”

45. Ṣùgbọ́n ó jáde lọ, ó bẹ̀rẹ̀ sí í pòkìkì, ó ń tan ìròyìn kálẹ̀. Nítorí èyí, Jésù kò sì le wọ ìlú ní gba-n-gba mọ́, ṣùgbọ́n ó wà lẹ́yìn odi ìlú ní ihà. Ṣíbẹ̀, àwọn ènìyàn tọ̀ ọ́ wá láti ibi gbogbo.

Ka pipe ipin Máàkù 1