Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Lúùkù 9:47-54 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

47. Nígbà tí Jésù sì mọ ìrò ọkàn wọn, ó mú ọmọdé kan, ó gbé e jókòó lọ́dọ̀ rẹ̀.

48. Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹnikẹ́ni tí ó bá gba ọmọdé yìí nítorí orúkọ mi, ó gbà mí: àti ẹnikẹ́ni tí ó bá gbà mí, ó gba ẹni tí ó rán mi: nítorí ẹni tí ó bá kéré jù nínú gbogbo yín, òun náà ni yóò pọ̀.”

49. Jòhánù sì dáhùn ó sì wí fún un pé, “Olùkọ́, àwá rí ẹnìkan ó ń fi orúkọ rẹ lé àwọn ẹ̀mí èsù jáde; àwa sì dá a lẹ́kun, nítorí tí kò bá wa tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.”

50. Jésù sì wí fún un, pé, “Má ṣe dá a lẹ́kun mọ́: nítorí ẹni tí kò bá lòdì síi yín, ó wà fún yín.”

51. Nígbà tí ọjọ́ àti gbà á sókè ń súnmọ́, ó fi ojú lé ọ̀nà láti lọ sí Jerúsálémù.

52. Ósì rán àwọn ìránṣẹ́ lọ sí iwájú rẹ̀: nígbà tí wọ́n sì lọ wọ́n wọ ìletò kan tí í ṣe ti ará Samaríà láti pèṣè sílẹ̀ dè é.

53. Wọn kò sì gbà á, nítorí ojú rẹ̀ dàbí ẹni pé ó ń lọ sí Jerúsálémù.

54. Nígbà tí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ Jákọ́bù àti Jòhánù sì rí i, wọ́n ní, “Olúwa wa, jẹ́ kí a pe iná láti ọ̀run wá, kí a sì pa wọ́n run, (bí Èlíjà ti ṣe?)”

Ka pipe ipin Lúùkù 9