Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Lúùkù 8:46-49 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

46. Jésù sì wí pé, “Ẹnìkan fi ọwọ́ kàn mí: nítorí tí èmí mọ̀ pé, àṣẹ jáde lára mi.”

47. Nígbà tí Obìnrin náà sì mọ̀ pé òun kò farasin, ó wárìrì, ó wá, ó sì wólẹ̀ níwájú rẹ̀, ó sì sọ fún un lójú àwọn ènìyàn gbogbo nítorí ohun tí ó ṣe, tí òun fi fi ọwọ́ kàn án, àti bí a ti mú òun láradá lójúkan náà.

48. Ó sì wí fún un pé, “Ọmọbìnrin, tújúká: ìgbàgbọ́ rẹ mú ọ láradá; máa lọ ní àlààáfíà!”

49. Bí ó sì ti ń sọ̀rọ̀ lẹ́nu, ẹnìkan ti ilé olórí sínágọ́gù wá, ó wí fún un pé, “Ọmọbìnrin rẹ kú; má yọ olùkọ́ni lẹ́nu mọ́.”

Ka pipe ipin Lúùkù 8