19. Nínú sùúrù yín ni ẹ̀yin ó jèrè ọkàn yín.
20. “Nígbà tí ẹ̀yin bá sì rí ti a fi ogun yí Jerúsálémù ká, ẹ mọ̀ nígbà náà pé, ìsọdahoro rẹ̀ kù sí dẹ̀dẹ̀.
21. Nígbà náà ni kí àwọn tí ń bẹ ní Jùdéà sá lọ sórí òkè; àti àwọn tí ń bẹ láàrin rẹ̀ kí wọn jáde kúrò; kí àwọn tí ó sì ń bọ̀ ní ìgbéríko má ṣe wọ inú rẹ̀ wá.