Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Lúùkù 2:48-52 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

48. Nígbà tí wọ́n sì rí i, háà ṣe wọ́n: ìyá rẹ̀ sì bi í pé, “Ọmọ, èéṣe tí ìwọ fi ṣe wá bẹ́ẹ̀? Sá wò ó, bàbá rẹ̀ àti èmi ti ń fi ìbìnújẹ́ wá ọ kiri.”

49. Ó sì dáhùn wí fún wọn pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi ń wá mi kiri, ẹ̀yin kò mọ̀ pé èmi kò lè ṣàìmá wà níbi iṣẹ́ Baba mi?”

50. Ọ̀rọ̀ tí sọ kò sì yé wọn.

51. Ó sì bá wọn sọ̀kalẹ̀ lọ sí Násárétì, sì fi ara balẹ̀ fún wọn: ṣùgbọ́n ìyá rẹ̀ pa gbogbo nǹkan wọ̀nyí mọ́ nínú ọkàn rẹ̀.

52. Jésù sì ń pọ̀ ní ọgbọ́n, sì ń dàgbà, ó sì wà ní ojúrere ní ọ̀dọ̀ Ọlọ́run àti ènìyàn.

Ka pipe ipin Lúùkù 2