Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Lúùkù 2:13-16 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

13. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ogun ọ̀run sì darapọ̀ mọ́ Ańgẹ́lì náà ní òjijì, wọ́n ń yin Ọlọ́run, wí pé,

14. “Ògo ni fún Ọlọ́run lókè ọ̀run,Àti ní ayé àlààáfíà, ìfẹ́ inú rere sí ènìyàn.”

15. Ó sì ṣe, nígbà tí àwọn ańgẹ́lì náà padà kúrò lọ́dọ̀ wọn lọ sí ọ̀run, àwọn Olùṣọ́-àgùntàn náà bá ara wọn sọ pé, “Ẹ jẹ́ kí á lọ tàrà sí Bẹ́tílẹ́hẹ́mù, kí á lè rí ohun tí ó ṣẹ̀ jẹ, tí Olúwa ti sọ nípa rẹ̀ fún wa.”

16. Wọ́n sì wá lọ́gán, wọ́n sì rí Màríà àti Jósẹ́fù, àti ọmọ-ọwọ́ náà, ó dùbúlẹ̀ nínú ibùjẹ ẹran.

Ka pipe ipin Lúùkù 2