Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Lúùkù 19:1-12 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Jésù sì wọ Jẹ́ríkò lọ, ó sì ń kọjá láàrin rẹ̀.

2. Sì kíyèsí i, ọkùnrin kan wà tí a ń pè ní Sákéù, ó sì jẹ́ olórí agbowó òde kan, ó sì jẹ́ ọlọ́rọ̀.

3. Ó sì ń fẹ́ láti rí ẹni tí Jésù jẹ́: kò sì lè rí i, nítrorí ọ̀pọ̀ ènìyàn, àti nítorí tí òun jẹ́ ènìyàn kúkúrú.

4. Ó sì súré ṣíwájú, ó gun orí igi síkámórè kan, kí ó bà lè rí i: nítorí tí yóò kọjá lọ níhà ibẹ̀.

5. Nígbà tí Jésù sì dé ibẹ̀, ó gbé ojú sókè, ó sì rí i, ó sì wí fún un pé, “Sákéù! Yára, kí o sì sọ̀kalẹ̀; nítorí pé èmi yóò wọ ilé rẹ lóní.”

6. Ó sì yára, ó sọ̀kalẹ̀, ó sì fi ayọ̀ gbà á.

7. Nígbà tí wọ́n sì rí i, gbogbo wọn ń kùn, wí pé, “Ó lọ wọ̀ lọ́dọ̀ ọkùnrin tí í ṣe ‘ẹlẹ́sẹ̀.’ ”

8. Sákéù sì dìde, ó sì wí fún Olúwa pé, “Wòó, Olúwa, ààbọ̀ ohun ìní mi ni mo fifún talákà; bí mo bá sì fi èké gba ohun kan lọ́wọ́ ẹnikẹ́ni, èmi san án padà ní ìlọ́po mẹ́rin!”

9. Jésù sì wí fún un pé, “Lóní ni ìgbàlà wọ ilé yìí, níwọ̀n bí òun pẹ̀lú ti jẹ́ ọmọ Ábúráhámù.

10. Nítorí Ọmọ Ènìyàn dé láti wá àwọn tí ó nù kiri, àti láti gbà wọ́n là.”

11. Nígbà tí wọ́n sì ń gbọ́ nǹkan wọ̀nyí, ó sì tẹ̀ṣíwájú láti pa òwe kan, nítorí tí ó súnmọ Jerúsálémù, àti nítorí tí wọn ń rò pé, ìjọba Ọlọ́run yóò farahàn nísinsin yìí.

12. Ó sì wí pé, “Ọkùnrin ọlọ́lá kan lọ sí ìlú òkèrè láti gba ìjọba kí ó sì padà.

Ka pipe ipin Lúùkù 19