Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Lúùkù 11:46-54 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

46. Ó sì wí pé, “Ègbé ni fún ẹ̀yin amòfin pẹ̀lú, nítorí tí ẹ̀yin di ẹrù tí ó wúwo láti rù lé ènìyàn lórí, bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin tìkarayín kò jẹ́ fi ìka yín kan ẹrù náà.

47. “Ègbé ni fún yín, nítorí tí ẹ̀yin kọ́ ibojì àwọn wòlíì, tí àwọn baba yín pa.

48. Ǹjẹ́ ẹ̀yin jẹ́ ẹlẹ́rìí, ẹ sì ní inú dídùn sí iṣẹ́ àwọn baba yín, nítorí tí wọn pa wọ́n, ẹ̀yin sì kọ́ ibojì wọn.

49. Nítorí èyí ni ọgbọ́n Ọlọ́run sì se wí pé, ‘Èmi ni ó rán àwọn wòlíì àti àwọn àpósítélì sí wọn, wọn ó sì ṣe inúnibíni sí wọn.’

50. Kí a lè bèèrè ẹ̀jẹ̀ àwọn wòlíì gbogbo, tí a ti ta sílẹ̀ láti ìgbà ìpilẹ̀ṣẹ̀ ayé wá, lọ́wọ́ ìran yìí;

51. Láti ẹ̀jẹ̀ Ábélì wá, títí ó sì fi dé ẹ̀jẹ̀ Sakaráyà, tí ó ṣègbé láàrin pẹpẹ àti tẹ́ḿpìlì: lóòótọ́ ni mo wí fún yín.

52. “Ègbé ni fún yín, ẹ̀yin amòfin, nítorí tí ẹ̀yin ti mú kọ́kọ́rọ́ ìmọ̀ kúrò; ẹ̀yin tìkára yín kò wọlé, àwọn tí sì ń wọlé, ni ẹ̀yin ń dí lọ́wọ́.”

53. Bí ó ti ń lọ kúrò níbẹ̀, àwọn akọ̀wé àti àwọn Farisí bẹ̀rẹ̀ sí bi í lọ́rọ̀ gidigidi, wọ́n sì ń yọ ọ́ lẹ́nu láti wí nǹkan púpọ̀.

54. Wọ́n ń ṣọ́ ọ, wọ́n ń wá ọ̀nà láti rí nǹkan gbámú mọ́ ọn lẹ́nu kí wọn báà lè fi ẹ̀sùn kàn án.

Ka pipe ipin Lúùkù 11