Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Lúùkù 11:41-46 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

41. Kí ẹ̀yin kúkú má a ṣe ìtọrẹ àánú nínú ohun tí ẹ̀yin ní, sì kíyèsii, ohun gbogbo ni ó di mímọ́ fún yín.

42. “Ṣùgbọ́n ègbé ni fún yín, ẹ̀yin Farisí, nítorí tí ẹ̀yin a máa san ìdámẹ́wàá mítì àti rue, àti gbogbo ewébẹ̀, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kọ ìdájọ́ àti ìfẹ́ Ọlọ́run: wọ̀nyí jẹ́ ohun tí ẹ gbọdọ̀ ṣe, láìsì fi àwọn ìyókù sílẹ̀ láìṣe.

43. “Ègbé ni fún yín, ẹ̀yin Farisí, àgàbàgebè! Nítorí tí ẹ̀yin fẹ́ ipò ọlá nínú sínágọ́gù, àti ìkíni ní ọjà.

44. “Ègbé ni fún-un yín, (ẹ̀yin akọ̀wé àti ẹ̀yin Farisí àgàbàgebè) nítorí ẹ̀yin dàbí ibojì tí kò farahàn, tí àwọn ènìyàn sì ń rìn lórí rẹ̀ láìmọ̀.”

45. Nígbà náà ni ọ̀kan nínú àwọn amòfin dáhùn, ó sì wí fún un pé, “Olùkọ́, nínú èyí tí ìwọ ń wí yìí ìwọ ń gan àwa pẹ̀lú.”

46. Ó sì wí pé, “Ègbé ni fún ẹ̀yin amòfin pẹ̀lú, nítorí tí ẹ̀yin di ẹrù tí ó wúwo láti rù lé ènìyàn lórí, bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin tìkarayín kò jẹ́ fi ìka yín kan ẹrù náà.

Ka pipe ipin Lúùkù 11