Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Lúùkù 1:38-53 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

38. “Màríà sì dáhùn wí pé, wò ó ọmọ-ọ̀dọ̀ Olúwa; kí ó rí fún mi gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.” Ańgẹ́lì náà sì fi í sílẹ̀ lọ.

39. Ní ijọ́ wọ̀nyí ni Màríà sì dìde, ó lọ kánkán sí ilẹ̀ òkè, sí ìlú kan ní Júdà;

40. Ó sì wọ ilé Sakaráyà lọ ó sì kí Èlísabẹ́tì.

41. Ó sì ṣe, nígbà tí Èlísábẹ́tì gbọ́ kíkí Màríà, ọlẹ̀ sọ nínú rẹ̀; Èlísábẹ́tì sì kún fún Èmí mímọ́;

42. Ó sì ké ní ohùn rara, ó sì wí pé, “Alúbùkún fún ni ìwọ nínú àwọn obìnrin, alábùkúnfún sì ni ọmọ tí ìwọ yóò bí.

43. Èéṣe tí èmi fi rí irú ojúrere yìí, tí ìyá Olúwa mi ìbá fi tọ̀ mí wá?

44. Sá wò ó, bí ohùn kíkí rẹ ti bọ́ sí mi ní etí, ọlẹ̀ sọ nínú mi fún ayọ̀.

45. Alábùkúnfún sì ni ẹni tí ó gbàgbọ́: nítorí nǹkan wọ̀nyí tí a ti sọ fún un láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá yóò ṣẹ.”

46. Màríà sì dáhùn, ó ní:“Ọkàn mi yin Olúwa lógo,

47. Ẹ̀mí mi sì yọ̀ sí Ọlọ́run Olùgbàlà mi.

48. Nítorí tí ó ṣíjú wo ìwà ìrẹ̀lẹ̀ọmọbìnrin ọ̀dọ̀ rẹ̀: Sá wò ó,láti ìsinsìn yìí lọ gbogbo ìran ènìyàn ni yóò máa pè mí ní alábùkúnfún.

49. Nítorí ẹni tí ó ní agbára ti ṣe ohun tí ó tóbi fún mi;Mímọ́ sì ni orúkọ rẹ̀.

50. Àánú rẹ̀ sì ń bẹ fún àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀láti ìrandíran.

51. Ó ti fi agbára hàn ní apá rẹ̀;Ó ti tú àwọn onígberaga ká ní ìrònú ọkàn wọn.

52. Ó ti mú àwọn alágbára kúrò lórí ìtẹ́ wọn,Ó sì gbé àwọn onírẹ̀lè lékè.

53. Ó ti fi ohun tí ó dára kún àwọn tí ebí ń paó sì rán àwọn ọlọ́rọ̀ padà ní òfo.

Ka pipe ipin Lúùkù 1