Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Lúùkù 1:36-41 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

36. Sì kíyèsí i, Èlísábẹ́tì ìbátan rẹ náà yóò sì ní ọmọ kùnrin kan ní ògbólògbó rẹ̀: èyí sì ni oṣù kẹfà fún ẹni tí à ń pè ní àgàn.

37. Nítorí kò sí ohun tí Ọlọ́run kò le ṣe.”

38. “Màríà sì dáhùn wí pé, wò ó ọmọ-ọ̀dọ̀ Olúwa; kí ó rí fún mi gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.” Ańgẹ́lì náà sì fi í sílẹ̀ lọ.

39. Ní ijọ́ wọ̀nyí ni Màríà sì dìde, ó lọ kánkán sí ilẹ̀ òkè, sí ìlú kan ní Júdà;

40. Ó sì wọ ilé Sakaráyà lọ ó sì kí Èlísabẹ́tì.

41. Ó sì ṣe, nígbà tí Èlísábẹ́tì gbọ́ kíkí Màríà, ọlẹ̀ sọ nínú rẹ̀; Èlísábẹ́tì sì kún fún Èmí mímọ́;

Ka pipe ipin Lúùkù 1