Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jòhánù 4:5-19 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

5. Nígbà náà ni ó dé ìlú Samaríà kan, tí a ń pè ní Síkárì, tí ó súnmọ́ etí ilẹ̀ oko tí Jákọ́bù ti fi fún Jóṣéfù, ọmọ rẹ̀.

6. Kànga Jákọ́bù sì wà níbẹ̀. Nítorí pé ó rẹ Jésù nítorí ìrìn rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ó jòkó létí kànga: ó sì jẹ́ ìwọ̀n wákàtí kẹfà ọjọ́.

7. Obìrin kan, ará Samaríà sì wá láti fà omi: Jésù wí fún un pé fún mi mu.

8. (Nítorí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ ti lọ sí ìlú láti lọ ra ońjẹ.)

9. Obìnrin ará Samáríà náà sọ fún un pé, “Júù ni ẹ́ obìnrin ará Samáríà ni èmi. Eéti rí tí ìwọ ń bèèrè ohun mímu lọ́wọ́ mi?” (Nítorí tí àwọn Júù kì í bá àwọn ará Samaríà ṣe pọ̀.)

10. Jésù dáhùn, ó sì wí fún un pé, “Ìbáṣepé ìwọ mọ ẹ̀bùn Ọlọ́run, ati ẹni tí ó wí fún ọ pé, fún mi mu, ìwọ ìbá sì ti bèèrè lọ́wọ́ rẹ̀, Òun ìbá ti fi omi ìyè fún ọ.”

11. Obìnrin náà wí fún un pé, “Alàgbà, ìwọ kò ní nǹkan tí ìwọ ó fi fà omi, bẹ́ẹ̀ ni kànga náà jìn: Níbo ni ìwọ ó ti rí omi ìyè náà?

12. Ìwọ pọ̀ ju Jákọ́bù baba wa lọ bí, ẹni tí ó fún wa ní kànga náà, tí Òun tìkararẹ̀ mu nínú rẹ̀, àti àwọn ọmọ rẹ̀, àti àwọn ẹran rẹ̀?”

13. Jésù dáhùn, ó sì wí fún un pé, “Ẹnikẹ́ni tí ó bá mu nínú omi yìí, òrùngbẹ yóò tún gbẹ ẹ́:

14. Ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí ó bá mu nínú omi tí èmi ó fí fún un, òrùngbẹ kì yóò gbẹ ẹ́ mọ́ láé; ṣùgbọ́n omi tí èmi ó fi fún un yóò di kànga omi nínú rẹ̀, tí yóò máa sun títí ayérayé.”

15. Obìnrin náà sì wí fún u pé, “Alàgbà, fún mi ní omi yìí, kí òùngbẹ kí ó má se gbẹ mí, kí èmi kí ó má sì wá máa pọn omi níbí.”

16. Jésù wí fún un pé, “Lọ pe ọkọ rẹ, kí ó sì padà wá sí ìhín yìí.”

17. Òbìnrin náà dáhùn, ó sì wí fún un pé, “Èmi kò ní ọkọ. Jésù wí fún un pé, Ìwọ́ dáhùn dáradára pé, èmi kò ní ọkọ:

18. Nítorí tí ìwọ ti ní ọkọ márùn-ún rí; ọkùnrin tí ìwọ sì ní bá yìí kì í ṣe ọkọ rẹ. Ohun tí ó ṣẹ̀ṣẹ̀ sọ tán yìí, òtítọ́ ni.”

19. Obìnrin náà wí fún un pé, “Alàgbà, mo wòye pé, wòlíì ni ìwọ ń ṣe.

Ka pipe ipin Jòhánù 4