Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jòhánù 4:18-23 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

18. Nítorí tí ìwọ ti ní ọkọ márùn-ún rí; ọkùnrin tí ìwọ sì ní bá yìí kì í ṣe ọkọ rẹ. Ohun tí ó ṣẹ̀ṣẹ̀ sọ tán yìí, òtítọ́ ni.”

19. Obìnrin náà wí fún un pé, “Alàgbà, mo wòye pé, wòlíì ni ìwọ ń ṣe.

20. Àwọn bàbá wa sìn lórí òkè yìí; ẹ̀yin sì wí pé, Jérúsálẹ́mù ni ibi tí ó yẹ tí à bá ti máa sìn.”

21. Jésù wí fún un pé, “Gbà mí gbọ́, obìnrin yìí, àkókò náà ń bọ̀, nígbà tí kì yóò se lórí òke yìí tàbí ní Jérúsálẹ́mù ni ẹ̀yin ó máa sin Baba.

22. Ẹ̀yin ń sin ohun tí ẹ̀yin kò mọ̀: àwa ń sin ohun tí àwa mọ̀: nítorí ìgbàlà ti ọ̀dọ̀ àwọn Júù wá.

23. Ṣùgbọ́n àkókò ń bọ̀, ó sì dé tán nísinsìn yìí, nígbà tí àwọn olùsìn tòótọ́ yóò máa sin Baba ní ẹ̀mí àti ní òtítọ́: nítorí irú wọn ni Baba ń wá kí ó máa sin òun.

Ka pipe ipin Jòhánù 4