Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jòhánù 3:26-36 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

26. Wọ́n sì tọ Jòhánù wá, wọ́n sì wí fún un pé, “Rábì, ẹni tí ó ti wà pẹ̀lú rẹ lókè odò Jọ́dánì, tí ìwọ ti jẹ́rí rẹ̀, wò ó, òun tẹ ni bọmi, gbogbo ènìyàn sì ń tọ̀ ọ́ wá.”

27. Jòhánù dáhùn ó sì wí pé, “Ènìyàn kò le rí ǹkankan gbà, bí kò ṣepé a bá ti fi fún ún láti ọ̀run wá.

28. Èyin fúnra yín jẹ́rìí mi, pé mo wí pé, ‘Èmi kì í ṣe Kírísítì náà, ṣùgbọ́n pé a rán mi ṣíwájú rẹ̀.’

29. Ẹni tí ó bá ni ìyàwó ni ọkọ ìyàwó; ṣùgbọ́n ọ̀rẹ́ ọkọ ìyàwó tí ó dúró tí ó sì ń gbóhùn rẹ̀, ó ń yọ̀ gidigidi nítorí ohùn ọkọ ìyàwó; nítorí náà ayọ̀ mi yí di kíkún.

30. Òun kò lè ṣàì máa pọ̀ sí i, ṣùgbọ́n èmi kò lè ṣàì má relẹ̀.

31. “Ẹni tí ó ti òkè wá ju gbogbo ènìyàn lọ; ẹni tí ó ti ayé wá ti ayé ni, a sì máa sọ ohun ti ayé. Ẹni tí ó ti ọ̀run wá ju gbogbo ènìyàn lọ.

32. Ohun tí ó ti rí tí ó sì ti gbọ́ èyí náà sì ni òun ń jẹ́rìí rẹ̀; kò sì sí ẹni tí ó gba ẹ̀rí rẹ̀.

33. Ẹni tí ó gba ẹ̀rí rẹ̀ fi èdìdì dì í pé, olótìítọ́ ni Ọlọ́run.

34. Nítorí ẹni tí Ọlọ́run ti rán ń sọ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run: nítorí tí Ọlọ́run fi Ẹ̀mí fún un láìsí gbèdéke.

35. Baba fẹ́ Ọmọ, ó sì ti fi ohun gbogbo lé e lọ́wọ́

36. Ẹni tí ó bá gba Ọmọ gbọ́, ó ní ìyè àìnípẹ̀kun: ẹni tí kò bá sì gba Ọmọ gbọ́, kì yóò rí ìyè; nítorí ìbínú Ọlọ́run ń bẹ lórí rẹ̀.”

Ka pipe ipin Jòhánù 3