21. Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá ń sọ òtítọ́ níí wá sí ìmọ́lẹ̀, kí iṣẹ́ rẹ̀ kí ó lè fi ara hàn pé a ṣe wọ́n nípa ti Ọlọ́run.”
22. Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, Jésù pẹ̀lú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ wá sí ilẹ̀ Jùdíà; ó sì dúró pẹ̀lú wọn níbẹ̀ ó sì ń ṣe ìtẹ̀bọmi fún ni.
23. Jòhánù pẹ̀lú sì ń ṣe ìtẹ̀bọmi ní Áhínónì, ní agbégbé Sálímù, nítorí tí omi púpọ̀ wà níbẹ̀: wọ́n sì ń wá, a sì ń tẹ̀ ẹ́ wọn bọmi.
24. Nítorí tí a kò tí ì sọ Jòhánù sínú túbú.
25. Nígbà náà ni iyàn kan wà láàárin àwọn ọmọ-ẹ̀yìn Jòhánù, àti Júù kan nípa ti ìwẹ̀nù.