Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jòhánù 20:1-13 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ní ọjọ́ kínní ọ̀ṣẹ̀ kùtùkùtù nígbà tí ilẹ̀ kò tíì mọ́ ni Màríà Magídalénè wá sí ibojì, ó sì rí i pé, a ti gbé òkúta kúrò lẹ́nu ibojì.

2. Nítorí náà, ó sáré, ó sì tọ Símónì Pétérù wá, àti ọmọ-ẹ̀yìn mìíràn náà ẹni tí Jésù fẹ́ràn, ó sì wí fún wọn pé, “Wọ́n ti gbé Olúwa kúrò nínú ibojì, àwa kò sì mọ ibi tí wọ́n gbé tẹ́ ẹ sí.”

3. Nígbà náà ni Pétérù jáde, àti ọmọ-ẹ̀yìn mìíràn náà, wọ́n sì wá sí ibojì.

4. Àwọn méjèèjì sì jùmọ̀ sáré: èyí ọmọ-ẹ̀yìn sì sáré ya Pétérù, ó sì kọ́kọ́ dé ibojì.

5. Ó sì bẹ̀rẹ̀ láti wo inú rẹ̀, ó rí aṣọ ọ̀gbọ̀ náà ní ilẹ̀; ṣùgbọ́n òun kò wọ inú rẹ̀.

6. Nígbà náà ni Símónì Pétérù tí ń bọ̀ lẹ́yìn rẹ̀ dé, ó sì wọ inú ibojì, ó sì rí aṣọ ọ̀gbọ̀ náà ní ilẹ̀.

7. Àti pé, gèlè tí ó wà níbi orí rẹ̀ kò sì wà pẹ̀lú aṣọ ọ̀gbọ̀ náà, ṣùgbọ́n o ká jọ ní ibìkan fúnra rẹ̀.

8. Nígbà náà ni ọmọ-ẹ̀yìn mìíràn náà, ẹni tí ó kọ́ dé ibojì wọ inú rẹ̀ pẹ̀lú, ó sì rí i ó sì gbàgbọ́.

9. (Nítorí tí wọn kò sáà tí mọ ìwé mímọ́ pé, òun ní láti jíǹde kúrò nínú òkú.)

10. Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ-ẹ̀yìn náà sì tún padà lọ sí ilé wọn.

11. Ṣùgbọ́n Màríà dúró létí ibojì lóde, ó ń sọkún: bí ó ti ń ṣọkún, bẹ́ẹ̀ ni ó bẹ̀rẹ̀, ó sì wo inú ibojì.

12. Ó sì kíyèsí àwọn áńgẹ́lì méjì aláṣọ funfun, wọ́n jókòó, ọ̀kan níhà orí àti ọ̀kan níhà ẹsẹ̀, níbi tí òkú Jésù gbé ti sùn sí.

13. Wọ́n sì wí fún un pé, “Obìnrin yìí, èé ṣe tí ìwọ fi ń sọkún?”Ó sì wí fún wọn pé, “Nítorí tí wọ́n ti gbé Olúwa mi, èmi kò sì mọ ibi tí wọ́n gbé tẹ́ ẹ sí.”

Ka pipe ipin Jòhánù 20