Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jòhánù 18:1-7 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Nígbà tí Jésù sì ti sọ nǹkan wọ̀nyí tán, ó jáde pẹ̀lú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ lọ sókè odò Kédírónì, níbi tí àgbàlá kan wà, nínú èyí tí ó wọ̀, Òun àti àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀.

2. Júdásì, ẹni tí ó dà á, sì mọ ibẹ̀ pẹ̀lú: nítorí nígbà púpọ̀ ni Jésù máa ń lọ síbẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀.

3. Nígbà náà ni Júdásì, lẹ́yìn tí ó ti gba ẹgbẹ́ ọmọ ogun, àti àwọn oníṣẹ́ láti ọ̀dọ̀ àwọn olórí àlùfáà àti àwọn Farisí wá síbẹ̀ ti àwọn ti fìtílà àti ògùṣọ̀, àti ohun ìjà.

4. Nítorí náà bí Jésù ti mọ ohun gbogbo tí ń bọ̀ wá bá òun, ó jáde lọ, ó sì wí fún wọn pé, “Ta ni ẹ ń wá?”

5. Wọ́n sì dá a lóhùn wí pé, “Jésù ti Násárétì.”Jésù sì wí fún wọn pé, “Èmi nìyí.” (Àti Júdásì ọ̀dàlẹ̀, dúró pẹ̀lú wọn.)

6. Nítorí náà bí ó ti wí fún wọn pé, “Èmi nìyí, wọ́n bì sẹ́yìn, wọ́n sì ṣubú lulẹ̀.”

7. Nítorí náà ó tún bi wọ́n léèrè, wí pé, “Ta ni ẹ ń wá?”Wọ́n sì wí pé, “Jésù ti Násárétì.”

Ka pipe ipin Jòhánù 18