Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jòhánù 13:33-38 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

33. “Ẹ̀yin ọmọ mi, nígbà díẹ̀ sí i ni èmi wà pẹ̀lú yín. Ẹ̀yin ó wá mi: àti gẹ́gẹ́ bí mo ti wí fún àwọn Júù pé, Níbití èmi gbé ń lọ, ẹ̀yin kì ó le wà; bẹ́ẹ̀ ni mo sì wí fún yín nísìnsìn yìí.

34. “Òfin titun kan ni mo fi fún yín, kí ẹ̀yin kí ó fẹ́ ọmọnìkejì yín; gẹ́gẹ́ bí èmi ti fẹ́ràn yín, kí ẹ̀yin kí ó sì lè fẹ́ràn ọmọnìkejì yín.

35. Nípa èyí ni gbogbo ènìyàn yóò fi mọ̀ pé, ọmọ-ẹ̀yìn mi ni ẹ̀yin ń se, nígbà tí ẹ̀yin bá ní ìfẹ́ sí ọmọ ẹnìkejì yín.”

36. Símónì Pétérù wí fún un pé, “Olúwa, níbo ni ìwọ ń lọ?”Jésù dá a lóhùn pé, “Níbi tí èmi ń lọ, ìwọ kì yóò lè tọ̀ mí nísinsin yìí; ṣùgbọ́n ìwọ yóò tọ̀ mí níkẹyìn.”

37. Pétérù wí fún un pé, “Olúwa èése tí èmi kò fi le tọ̀ ọ́ nísinsìn yìí? Èmi ó fi ẹ̀mi mi lélẹ̀ nítorí rẹ.”

38. Jésù da lóhùn wí pé, “Ìwọ ó ha fi ẹ̀mí rẹ lélẹ̀ nítorí mi? Lóòótọ́ lóòótọ́ ni mo wí fún ọ, àkùkọ kì yóò kọ, kí ìwọ kí ó tó ṣẹ́ mi nígbà mẹ́ta!

Ka pipe ipin Jòhánù 13