Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jòhánù 12:28-41 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

28. Baba, ṣe orúkọ rẹ lógo!”Nígbà náà ni ohùn kan ti ọ̀run wá, wí pé, “Èmi ti ṣe é lógo!”

29. Nítorí náà ìjọ ènìyàn tí ó dúró níbẹ̀, tí wọ́n sì gbọ́ ọ, wí pé, àrá ń sán: àwọn ẹlòmíràn wí pé, “Ańgẹ́lì kan ni ó ń bá a sọ̀rọ̀.”

30. Jésù sì dáhùn wí pé, “Kì í ṣe nítorí mi ni ohùn yìí ṣe wá, bí kò ṣe nítorí yín.

31. Ní ìsinsin yìí ni ìdájọ́ ayé yìí dé: nísinsin yìí ni a ó lé aládé ayé yìí jáde.

32. Àti èmi, bí a bá gbé mi sókè èmi ó fa gbogbo ènìyàn sọ́dọ̀ ara mi!”

33. Ṣùgbọ́n ó wí èyí, ó ń ṣàpẹrẹ irú ikú tí òun ó kú.

34. Nítorí náà àwọn ìjọ ènìyàn dá a lóhùn pé, “Àwa gbọ́ nínú òfin pé, Kírísítì wà títí láéláé: ìwọ ha ṣe wí pé, ‘A ó gbé ọmọ ènìyàn sókè? Ta ni ó ń jẹ́ ọmọ ènìyàn yìí’?”

35. Nígbà náà ni Jésù wí fún wọn pé, “Nígbà díẹ̀ sí i ni ìmọ́lẹ̀ wà láàárin yín, ẹ máa rìn nígbà tí ẹ̀yin ní ìmọ́lẹ̀, kí òkùnkùn má ṣe bá yín: ẹni tí ó bá sì ń rìn ní òkùnkùn kò mọ ibi òun gbé ń lọ.

36. Nígbà tí ẹ̀yin ní ìmọ́lẹ̀, ẹ gba ìmọ́lẹ̀ gbọ́, kí ẹ lè jẹ́ ọmọ ìmọ́lẹ̀!” Nǹkan wọ̀nyí ni Jésù sọ, ó sì jáde lọ, ó fi ara pamọ́ fún wọn.

37. Ṣùgbọ́n bí ó ti ṣe ọ̀pọ̀lọpọ̀ iṣẹ́ àmì tó báyìí lójú wọn, wọn kò gbà á gbọ́.

38. Kí ọ̀rọ̀ wòlíì Ìsàíàh lè ṣẹ, èyí tí ó sọ pé:“Olúwa, tani ó gba ìwàásù wa gbọ́Àti ta ni a sì fi apá Olúwa hàn fún?”

39. Nítorí èyí ni wọn kò fi lè gbàgbọ́, nítorí Ìsáyà sì tún sọ pé:

40. “Ó ti fọ́ wọn lójú,Ó sì ti sé àyà wọn le;Kí wọn má baà fi ojú wọn rí,Kí wọn má ba à fi ọkàn wọn mọ̀,Kí wọn má baà yípadà, kí wọn má baà mú wọn láradá.”

41. Nǹkan wọ̀nyí ni Ìsáyà wí, nítorí ó ti rí ògo rẹ̀, ó sì sọ̀rọ̀ rẹ̀.

Ka pipe ipin Jòhánù 12