10. Ṣùgbọ́n àwọn olórí àlùfáà gbìmọ̀ kí wọn lè pa Lásárù pẹ̀lú;
11. Nítòrí pé nípasẹ̀ rẹ̀ ni ọ̀pọ̀ nínú àwọn Júù jáde lọ, wọ́n sì gbà Jésù gbọ́.
12. Ní ijọ kejì nígbà tí ọ̀pọ̀ ènìyàn tí ó wá sí àjọ gbọ́ pé, Jésù ń bọ̀ wá sí Jérúsálẹ́mù.
13. Wọ́n mú imọ̀ ọ̀pẹ, wọ́n sì jáde lọ pàdé rẹ̀, wọ́n sì ń kígbe pé,“Hòsánnà!”“Olùbùkún ni ẹni tí ń bọ̀wá ní orúkọ Olúwa, ọba Ísríẹ́lì!”
14. Nígbà tí Jésù sì rí ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ kan, ógùn ún; gẹ́gẹ́ bí a ti kọ̀wé pé,
15. “Má bẹ̀rù, ọmọbìnrin Síónì;Wò ó, ọba rẹ ń bọ̀ wá,Ó jókòó lórí ọmọ kẹ́tẹ́ktẹ́.”
16. Nǹkan wọ̀nyí kò tètè yé àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀: ṣùgbọ́n nígbà tí a ṣe Jésù lógo, nígbà náà ni wọ́n rántí pé, a kọ̀wé ǹkan wọ̀nyí nípa rẹ̀ sí i.