Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jòhánù 12:1-7 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Nítorí náà, nígbà tí àjọ ìrékọjá ku ìjọ́ mẹ́fà, Jésù wá sí Bẹ́tanì, níbi tí Lásárù wà, ẹni tí ó ti kú, tí Jésù jí dìde kúrò nínú òkú.

2. Wọ́n sì se àṣè alẹ́ fún un níbẹ̀: Màtá sì ń ṣe ìránṣẹ́: ṣùgbọ́n Lásárù Jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn tí ó jókòó níbi tábìlì rẹ̀.

3. Nígbà náà, Màtá mú òróró ìkunra nádì, òṣùwọ̀n lítà kan, àìlábùlà, olówó iyebíye, ó sì ń fi kun Jésù ní ẹṣẹ̀, ó sì ń fi irun orí rẹ̀ nu ẹṣẹ̀ rẹ̀ nù: ilẹ̀ sì kún fún òórùn ìkunra náà.

4. Nígbà náà ni ọ̀kan nínú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, Júdásì Isíkáríótù, ọmọ Símónì ẹni tí yóò fi í hàn, wí pé,

5. “Èé ṣe tí a kò ta òróró ìkunra yìí ní ọ̀ọ́dúnrún owó idẹ kí a sì fi fún àwọn talákà?”

6. Ṣùgbọ́n ó wí èyí, kì í ṣe nítorí tí ó náání àwọn talákà; ṣùgbọ́n nítorí tí ó jẹ́ olè, òun ni ó sì ní àpò, a sì máa gbé ohun tí a fi sínú rẹ̀.

7. Nígbà náà ni Jésù wí pé, “Ẹ fi í sílẹ̀, ó ṣe é sílẹ̀ de ọjọ́ ìsìnkú mi.

Ka pipe ipin Jòhánù 12