Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìfihàn 8:11-13 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

11. A sì ń pe orúkọ ìràwọ̀ náà ni ìwọ̀, ìdámẹ̀ta àwọn omi sì di ìwọ̀, ọ̀pọ̀lọ́pọ̀ ènìyàn sì tí ipa àwọn omi náà kú, nítorí tí a sọ wọn di kíkorò.

12. Ańgẹ́lì kẹ́rin sì fún ìpè tirẹ̀, a sì kọlu ìdámẹ̀ta òòrùn, àti ìdámẹ̀ta òṣùpá, àti ìdámẹ̀ta àwọn ìràwọ̀, ki ìdámẹ̀ta wọn lè ṣóòkùn, kí ọjọ́ má ṣe mọ́lẹ̀ fún ìdámẹ̀ta rẹ̀, àti òru báka náà.

13. Mo sì wò, mo sì gbọ́ idí kan tí ń fò ni àárin ọ̀run, ó ń wí lóhùn rara pé, “Ègbé, ègbé, fún àwọn tí ń gbé orí ilẹ̀ ayé nítorí ohun ìpè ìyókù tí àwọn ańgẹ́lì mẹ́ta tí ń bọ̀ wá yóò fún!”

Ka pipe ipin Ìfihàn 8