Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìfihàn 18:1-4 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí mo sì rí ańgẹ́lì mìíràn, ó ń ti ọ̀run sọkalẹ̀ wá ti òun ti agbára ńlá; ilẹ̀ ayé sì ti ipa ògo rẹ̀ mọ́lẹ̀.

2. Ó sì kígbe ní ohùn rara, wí pé:“Bábílónì ńlá ṣubú! Ó ṣubú!Ó sì di ibùjókòó àwọn ẹ̀mí ẹ̀ṣù,àti ihò ẹ̀mí àìmọ́ gbogbo,àti ilé ẹyẹ àìmọ́ gbogbo,àti ti ẹyẹ ìríra.

3. Nítorí nípa ọtí wáìnì ìrunú àgbèrè rẹ̀ nigbogbo àwọn orílẹ̀-èdè ṣubú.Àwọn ọba ayé sì ti bá a ṣe àgbèrè,àti àwọn oníṣòwò ayé sì di ọlọ́rọ̀ nípa ọ̀pọ̀lọpọ̀ wọ̀bìà rẹ̀.”

4. Mo sì gbọ́ ohùn mìíràn láti ọ̀run wá, wí pé:“Ẹ ti inú rẹ̀ jáde, ẹ̀yin ènìyàn mi,kí ẹ ma bàá ṣe alábàápín nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀,kí ẹ ma bàá si ṣe gbà nínú ìyọnu rẹ̀.

Ka pipe ipin Ìfihàn 18