Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìṣe Àwọn Àpósítélì 25:16-27 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

16. “Àwọn ẹni tí mo sì dá lóhùn pé, kì í ṣe àṣà àwọn ará Róòmù láti dá ẹnìkẹ́ni lẹ́bí, kí ẹni tí a fiṣùn náà tó ko àwọn olùfisùn rẹ̀ lójú, láti lè ri àyè wí tí ẹnu rẹ̀, nítorí ọ̀ràn tí a kà sí i lọ́rùn,

17. Nítorí náà nígbà tí wọ́n jùmọ̀ wá sí ìhín yìí, èmi kò fi ọ̀rọ̀ náà falẹ̀ rara, níjọ́ kéjì mo jókòó lórí ìtẹ́ ìdájọ́, mo sì pàṣẹ pé kí a mú ọkùnrin náà wá.

18. Nígbà tí àwọn olùfiṣùn náa dìde, wọn kò ka ọ̀ràn búburú irú èyí tí mo rò sí i lọ́rùn.

19. Ṣùgbọ́n wọ́n ní ọ̀ràn kan sí i, ní ti ìsìn wọn, àti ní ti Jésù kan tí o tí kú, tí Pọ́ọ̀lù tẹnumọ́ pé ó wà láàyè.

20. Bí èmi kò sì tí mọ̀ bí a tí ń se ìwàdìí nǹkan wọ̀nyí, mo bí i lere pé ṣe ó ń fẹ́ lọ sì Jerúsálémù, kí a sì ṣe ẹjọ́ nǹkan wọ̀nyí níbẹ̀.

21. Ṣùgbọ̀n nígbà tí Pọ́ọ̀lù fi ọ̀ràn rẹ lọ Ọ̀gọ́sítù, pé kí a pa òun mọ́ fún ìdájọ́ rẹ̀, mo pàṣẹ pé kí a pa á mọ́ títí èmi o fi lè rán an lọ sọ́dọ̀ Késárì.”

22. Àgírípà sí wí fún Fésítúsì pé, “Èmi pẹ̀lú fẹ́ láti gbọ ọ̀rọ̀ ọkùnrin náà tìkááramì,” Ó sì wí pé, “Ní ọ̀la ìwọ ó gbọ́ ọ.”

23. Ní ọjọ́ kejì, tí Àgírípà àti Báníkè wọ ilé ẹjọ́ ti àwọn ti ẹ̀sọ́ púpọ̀ pẹ̀lú àwọn olórí ogun àti àwọn ènìyàn ńlá ní ìlú, Fẹ́sítúsì pàṣẹ, wọ́n sì mú Pọ́ọ̀lù jáde.

24. Fẹ́sítúsì sì wí pé, “Àgírípà Ọba, àti gbogbo ẹ̀yin ènìyàn tí ó wà níhìn pẹ̀lú wa, ẹ̀yin rí ọkùnrin yìí, nítorí ẹni tí gbogbo ìjọ àwọn Júù tí fi ẹ̀bẹ̀ bèèrè lọ́wọ́ mi ni Jerúsálémù àti Kesaríà níhìn yìí, tí wọ́n ń kígbe pé, kò yẹ fún un láti wà láàyè mọ́.

25. Ṣùgbọ́n èmi rí i pé, kò se ohun kan tí ó yẹ sí ikú, bí òun tìkárarẹ̀ sí tí fi ọ̀ràn rẹ̀ lọ Aúgọ́sítù, mo tí pinnu láti rán an lọ.

26. Ṣùgbọ́n èmi kò ri ohun kan dájúdájú láti kọ̀wé sí olúwa mi. Nítorí náà ni mo ṣe mú un jáde wá ṣíwájú yín, àní ṣíwájú rẹ ọba Àgírípà, kí o fi jẹ́ pé lẹ́yìn tí a ba tí se wádìí rẹ̀, èmi yóò lè rí ohun tí èmi yóò kọ.

27. Nítorí tí kò tọ́ ní ojú mi láti rán òǹdè, kí a má sì sọ ọ̀ràn tí a kà sí i lọ́rùn.”

Ka pipe ipin Ìṣe Àwọn Àpósítélì 25