Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìṣe Àwọn Àpósítélì 21:30-39 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

30. Gbogbo ìlú sì wà ní ìrúkèrúdo, àwọn ènìyàn sì súré jọ: wọ́n sì mú Pọ́ọ̀lù, wọ́n sì wọ́ ọ jáde kúrò nínú tẹ́ḿpílì: lójúkan náà, a sì ti ìlẹ̀kùn.

31. Bí wọn sì ti ń wá ọ̀nà láti pa á, ìròyìn dé ọ̀dọ̀ olórí ẹgbẹ́ ọmọ-ogun pé, gbogbo Jerúsálémù dàrú.

32. Lójúkan náà, ó sì ti mú àwọn ọmọ-ogun àti àwọn balógun ọ̀rún, ó sì súré sọ̀kalẹ̀ tọ̀ wọ́n lọ; nígbà tí wọ́n sì rí í olórí ogun àti àwọn ọmọ-ogun dẹ́kun lílù Pọ́ọ̀lù.

33. Nígbà náà ni olórí ogun súnmọ́ wọn, ó sì mú un, ó pàṣẹ pé kí a fi ẹ̀wọ̀n méjì dè é; ó sì bèèrè ẹni tí ó jẹ́, àti ohun tí ó ṣe.

34. Àwọn kan ń kígbe ohun kan, àwọn mìíràn ń kígbe ohun mìíràn nínú àwùjọ; nígbà tí kò sì lè mọ̀ ìdí pàtàkì fún ìrúkèrúdò náà, ó pàṣẹ kí wọ́n mú un lọ sínú àgọ́ àwọn ológun.

35. Nígbà tí ó sì dé orí àtẹ̀gùn, gbígbé ni a gbé e sókè lọ́wọ́ àwọn ọmọ-ogun nítorí ìwà-ipá àwọn ènìyàn.

36. Nítorí ọ̀pọ̀ ènìyàn rọ́ tẹ̀lé e, wọ́n ń kígbe pé, “Mú un kúrò!”

37. Bí wọ́n sì tí fẹ́rẹ̀ mú Pọ́ọ̀lù wọ inú àgọ́ àwọn ológun lọ, ó wí fún olórí-ogun pé, “Èmi ha lè bá ọ sọ̀rọ̀ bí?”Ó sì dáhùn wí pé, “Ìwọ mọ èdè Gíríkì bí?

38. Ìwọ ha kọ ní ara Íjíbítì náà, tí ó ṣọ̀tẹ̀ ṣáájú ọjọ́ wọ̀nyí, ti ó sì ti mú ẹgbàajì ọkùnrin nínú àwọn tí í ṣe apànìyàn lẹ́yìn lọ ṣí ijù?”

39. Ṣùgbọ̀n Pọ́ọ̀lù sì wí pé, “Júù ní èmi jẹ́, ará Tásọ́sì ilú Kílíkíà, tí kì í ṣe ìlú yẹpẹrẹ kan, èmi ṣí bẹ̀ ọ, fún mi ní ààyè láti bá àwọn ènìyàn wọ̀nyí sọ̀rọ̀!”

Ka pipe ipin Ìṣe Àwọn Àpósítélì 21