Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìṣe Àwọn Àpósítélì 19:30-34 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

30. Nígbà ti Pọ́ọ̀lù sì ń fẹ́ wọ àárin àwọn ènìyàn lọ, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn kọ̀ fún un.

31. Àwọn olórí kan ara Éṣíà, tí i ṣe ọ̀rẹ́ rẹ̀, ránṣẹ́ sí i, wọ́n bẹ̀ ẹ́ pé, kí ó má ṣe fi ara rẹ̀ wéwu nínú ilé ibi-ìṣeré náà.

32. Ǹjẹ́ àwọn kan ń wí ohun kan, àwọn mìíràn ń wí òmíran: nítorí àjọ di rúdurùdu; ọ̀pọ̀ ènìyàn ni kò sì mọ̀ ìdí ohun tí wọ́n tilẹ̀ fi péjọ pọ̀.

33. Àwọn kan nínú àwujọ ń gún Alekisáńdérù, tí àwọn Júù tì síwájú, ní kẹ́ṣẹ́ láti ṣọ̀rọ̀ Alekisáńdérù sì juwọ́ sì wọn, òun ìbá sì wí ti ẹnu rẹ̀ fún àwọn ènìyàn.

34. Ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n mọ̀ pé Júù ni, gbogbo wọn, ni ohùn kan, bẹ̀rẹ̀ ṣí kígbe fún bi wákàtí méjì pé, “Òrìṣà ńlá ni Dáyánà tí ará Éfésù!”

Ka pipe ipin Ìṣe Àwọn Àpósítélì 19