Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìṣe Àwọn Àpósítélì 19:13-16 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

13. Ṣùgbọ́n àwọn Júù kan alárìnkiri, alẹ́mìí-èṣù jáde, bẹ̀rẹ̀ rẹ̀ ni àdábọwọ́ ara wọn, láti pé orúkọ Jésù Olúwa sí àwọn tí ó ni ẹ̀mí búburú, wí pé, “Àwa fi orúkọ Jésù tí Pọ́ọ̀lù ń wàásù fi yín bú.”

14. Àwọn méje kan sì wà, tí wọn ń ṣe bẹ́ẹ̀, àwọn ọmọ ẹnìkan tí a ń pè ni Síkẹ́fà, Júù, tí í ṣe olórí àlùfáà gíga.

15. Ẹmí búburú náà sì dáhùn, ó ní “Jéù èmi mọ̀ ọ́n, mo sì mọ Pọ́ọ̀lù pẹ̀lú, ṣùgbọ́n ta ni ẹ̀yin?”

16. Nígbà tí ọkùnrin tí ẹ̀mí búburú náà wà lára rẹ̀ sì fò mọ́ wọn, ó pá kúúrù mọ́ wọn, ó sì borí wọn, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sá jáde kúrò ní ilé náà ní ìhòòhò pẹ̀lú ni ìfarapa.

Ka pipe ipin Ìṣe Àwọn Àpósítélì 19