Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìṣe Àwọn Àpósítélì 19:1-5 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Nígbà ti Àpólò wà ni Kọ́ríńtì, ti Pọ́ọ̀lù kọjá lọ sí apá òkè-ìlú, ó sì wá ṣí Éfésù: o sì rí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn kan;

2. Ó wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin ha gba Ẹ̀mi Mímọ́ náà nígbà tí ẹ̀yin gbàgbọ́?”Wọ́n sì wí fún un pé, “Àwa kò gbọ́ rárá pé Ẹ̀mí Mímọ́ kan wà.”

3. Ó sì wí pé, “Ǹjẹ́ irú bamítíìsímù wo ni a bamitíìsímù yín sí?”Wọ́n sì wí pé, “Sí bamitíìsímù tí Jòhánù.”

4. Pọ́ọ̀lù sí wí pé, “Nítọ̀ọ́tọ́, ní Jòhánù fi bamitíìsímù tí ìrònúpìwàdà bamitíìsímù, ó ń wí fún àwọn ènìyàn pé, kí wọ́n gba ẹni tí ń bọ̀ lẹ́yìn òun gbọ́, èyí sì ni Kírísítì Jésù.”

5. Nígbà tí wọ́n sì gbọ́, a bamitíìsímù wọn lórúkọ Jéṣù Olúwa.

Ka pipe ipin Ìṣe Àwọn Àpósítélì 19