Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìṣe Àwọn Àpósítélì 18:13-18 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

13. Wọ́n wí pé, “Ọkùnrin yìí ń yí àwọn ènìyàn lọ́kàn padà, láti máa sin Ọlọ́run lòdì sí òfin.”

14. Nígbà tí Pọ́ọ̀lù ń fẹ́ dáhùn, Gálíónì wí fún àwọn Júù pé, “Ìbá ṣe pé ọ̀ràn búburú tàbí tí jàgídíjàgan kan ni, èmi ìbá gbè yín, ẹyin Júù;

15. Ṣùgbọ́n bí ó ti ṣe ọ̀ràn nipa ọ̀rọ̀ àti orúkọ, àti ti òfin yín ni, ki ẹ̀yin bojútó o fúnrará yín; nítorí tí èmi kò fẹ ṣe onídàjọ́ nǹkan báwọ̀nyí.”

16. Ó sì lé wọn kúrò ní ibi ìtẹ́ ìdájọ́.

17. Gbogbo àwọn Gíríkì sì mú Sósìténì, olórí ṣínágógù, wọ́n sì lù ú níwájú ìtẹ́ ìdájọ́. Gálíónì kò sì bìkítà fún nǹkan wọ̀nyí.

18. Pọ́ọ̀lù sì dúró sí i níbẹ̀ lọ́jọ́ púpọ̀, nígbà tí ó sì dágbére fún àwọn arákùnrin, ó bá ọkọ̀-ojúomi lọ si Síríà, àti Pìrìsílà àti Àkúílà pẹ̀lú rẹ̀; ó tí fá orí rẹ̀ ni Kéníkíríà: nítorí tí o tí jẹ́jẹ̀ẹ́.

Ka pipe ipin Ìṣe Àwọn Àpósítélì 18