Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìṣe Àwọn Àpósítélì 15:24-35 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

24. Níwọ̀n bí àwa ti gbọ́ pé, àwọn kan ti ó ti ọ̀dọ̀ wa jáde wá ń fi ọ̀rọ̀ yọ yín lẹ́nu, tí wọ́n ń yí yín lọ́kàn po, (wí pé, Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ ṣàìmá kọ ilà, àti ṣaima pa òfin Mósè mọ́:) ẹni tí àwa kò fún ní àṣẹ:

25. Ó yẹ lójú àwa, bí àwa ti fi ìmọ̀ sọ̀kan láti yan ènìyàn láti rán wọn sí yín, pẹ̀lú Bánábà àti Pọ́ọ̀lù àwọn olùfẹ́ wa.

26. Àwọn ọkùnrin ti ó fi ọkàn wọn wéwu nítorí orúkọ Olúwa wa Jésù Kírísítì.

27. Nítorí náà àwa rán Júdà àti Sílà àwọn tí yóò sì fi ọ̀rọ̀ ẹnu sọ ohun kan náà fún yín.

28. Nítorí ó dára lójú Ẹ̀mí Mímọ́, àti lójú wa, kí a má ṣe di ẹrù kà yín, bí kò ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí tí ó ṣe pàtàkì;

29. Kí ẹ̀yin fà sẹ̀yìn kúrò nínú ẹran àpabọ òrìṣà, àti nínú ẹ̀jẹ̀ àti nínú ohun ìlọ́lọ́rùn-pa, àti nínú àgbérè: nínú ohun tí, bí ẹ̀yin bá pa ara yín mọ́ kúrò, ẹ̀yin ó ṣe rere.Àlàáfíà.

30. Ǹjẹ́ nígbà tí wọ́n sì fi wọ́n sílẹ̀ láti lọ, wọ́n sọ̀kalẹ̀ wá si Áńtíókù: nígbà tí wọn sì pé àwọn ìjọ pọ̀, wọn fi ìwé náà fún wọn.

31. Nígbà tí wọn sì kà á, wọ́n yọ̀ fún ìtùnú náà.

32. Bí Júdà àti Sílà tìkara wọn ti jẹ́ wòlíì pẹ̀lú, wọ́n fi ọ̀rọ̀ púpọ̀ gba àwọn arákùnrin níyànjú, wọ́n sì mú wọn lọ́kàn le.

33. Nígbà tí wọn sì pẹ́, díẹ̀, àwọn arákùnrin rán wọn padà lọ ni àlàáfíà sí ọ̀dọ̀ àwọn tí ó rán wọn wá.

34. (Ṣùgbọ́n o wú Sílà láti gbé ibẹ̀.)

35. Pọ́ọ̀lù àti Bánábà sì dúró díẹ̀ ni Ańtíókù, wọ́n ń kọ́ní, wọ́n sì ń wàásù ọ̀rọ̀, Olúwa, àti àwọn púpọ̀ mìíràn pẹ̀lú wọn.

Ka pipe ipin Ìṣe Àwọn Àpósítélì 15