Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìṣe Àwọn Àpósítélì 15:12-25 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

12. Gbogbo àjọ sí dákẹ́, wọ́n sì fi ẹ̀rí sí Bánábà àti Pọ́ọ̀lù, tí wọn ń ròyìn iṣẹ́-àṣẹ àti iṣẹ́-àmì tí Ọlọ́run tí ti ọwọ́ wọn ṣe láàrin àwọn aláìkọlà.

13. Lẹ̀yìn tí wọn sì dákẹ́, Jákọ́bù dáhùn, wí pé, “Ará, ẹ gbọ́ tèmi:

14. Símóòní ti róyìn bí Ọlọ́run ti kọ́kọ́ bojúwo àwọn aláìkọlà, láti yàn ènìyàn nínú wọn fún orúkọ rẹ̀.

15. Báyìí ni ọ̀rọ̀ àwọn wòlíì bá ṣe dédé; bí a ti kọ̀wé rẹ̀ pé:

16. “ ‘Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí ni èmi ó padà,èmi ó sì tún àgọ́ Dáfídì pa tí ó ti wó lulẹ̀:èmi ó sì tún ahoro rẹ̀ kọ́,èmi ó sì gbé e ró:

17. kí àwọn ènìyàn ìyókù lè máa wá Olúwa,àti gbogbo àwọn aláìkọlà tí a ń fi orúkọ mi pè.’ni Olúwa wí, ta ni ó ń ṣe nǹkan wọ̀nyí

18. Ní Olúwa wí, ẹni tí ó sọ gbogbonǹkan wọ̀nyí di mímọ́ láti ọjọ́ pípẹ́ wá,

19. “Ǹjẹ́ ìmọ̀ràn tèmi ni pé, kí a máa ṣe yọ àwọn ti aláìkọlà ti ó yípadà sí Ọlọ́run lẹ́nu.

20. Ṣùgbọ́n kí a kọ̀wé si wọn, kí wọ́n fà sẹ̀hín kúrò nínú èérí òrìṣà, àti kúrò nínú àgbèrè, àti nínú ẹ̀jẹ̀.

21. Mósè nígbà àtijọ́, sá ní àwọn ti ń wàásù rẹ̀, ni ìlú gbogbo, a máa ń kà á nínú sínágọ́gù ni ọjọ́jọ́ ìsinmi.”

22. Nígbà nàá ni ó tọ́ lójú àwọn àpósítélì, àti àwọn alàgbà pẹ̀lú gbogbo ìjọ, láti yan ènìyàn nínú wọn, àti láti rán wọ́n lọ sí Áńtíókù pẹ̀lú Pọ́ọ̀lù àti Bánábà: Júdà ti a ń pè àpèlé rẹ̀ ní Básábà, àti Sílà, ẹni tí ó lórúkọ nínú àwọn arákùnrin.

23. Wọn sì kọ ìwé lé wọn lọ́wọ́ báyìí pé:Àwọn àpósítélì, àti àwọn alàgbà,Tí ó jẹ̀ ti aláìkọlà tí ó wà ní Áńtíókù, àti ní Síríà: àti ní Kílíkíà.

24. Níwọ̀n bí àwa ti gbọ́ pé, àwọn kan ti ó ti ọ̀dọ̀ wa jáde wá ń fi ọ̀rọ̀ yọ yín lẹ́nu, tí wọ́n ń yí yín lọ́kàn po, (wí pé, Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ ṣàìmá kọ ilà, àti ṣaima pa òfin Mósè mọ́:) ẹni tí àwa kò fún ní àṣẹ:

25. Ó yẹ lójú àwa, bí àwa ti fi ìmọ̀ sọ̀kan láti yan ènìyàn láti rán wọn sí yín, pẹ̀lú Bánábà àti Pọ́ọ̀lù àwọn olùfẹ́ wa.

Ka pipe ipin Ìṣe Àwọn Àpósítélì 15