11. Ṣùgbọ́n àwa gbàgbọ́ pé nípa oore-ọ̀fẹ́ Olúwa Jésù àwa ó là, gẹ́gẹ́ bí àwọn.”
12. Gbogbo àjọ sí dákẹ́, wọ́n sì fi ẹ̀rí sí Bánábà àti Pọ́ọ̀lù, tí wọn ń ròyìn iṣẹ́-àṣẹ àti iṣẹ́-àmì tí Ọlọ́run tí ti ọwọ́ wọn ṣe láàrin àwọn aláìkọlà.
13. Lẹ̀yìn tí wọn sì dákẹ́, Jákọ́bù dáhùn, wí pé, “Ará, ẹ gbọ́ tèmi:
14. Símóòní ti róyìn bí Ọlọ́run ti kọ́kọ́ bojúwo àwọn aláìkọlà, láti yàn ènìyàn nínú wọn fún orúkọ rẹ̀.
15. Báyìí ni ọ̀rọ̀ àwọn wòlíì bá ṣe dédé; bí a ti kọ̀wé rẹ̀ pé:
16. “ ‘Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí ni èmi ó padà,èmi ó sì tún àgọ́ Dáfídì pa tí ó ti wó lulẹ̀:èmi ó sì tún ahoro rẹ̀ kọ́,èmi ó sì gbé e ró: