Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Gálátíà 5:1-6 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Nítorí náà, ẹ dúró ṣinṣin nínú òmìnira náà èyí tí Kírísítì fi sọ wá di òmìnira, kí ẹ má sì ṣe tún fi ọrùn bọ̀ àjàgà ẹrú mọ́.

2. Kíyèsí i, èmi Pọ́ọ̀lù ni ó wí fún yín pé, bí a bá kọ yín nílà, Kírísítì kì yóò lérè fún yín ní ohunkóhun.

3. Mo sì tún sọ fún olúkúlùkù ènìyàn tí a kọ ní ilà pé, ó di ajigbésè láti pa gbogbo òfin mọ́.

4. A ti yà yín kúrò lọ́dọ̀ Kírísítì, ẹ̀yin tí ń fẹ́ kí a dá yín láre nípa òfin; pé ẹ ti ṣubú kúrò nínú oore-ọ̀fẹ́.

5. Nítorí nípa Ẹ̀mí àwa ń fi ìgbàgbọ́ dúró de ìrètí òdodo.

6. Nítorí nínú Kírísítì Jésù ìkọlà kò jẹ́ ohun kan, tàbí àìkọlà; ṣùgbọ́n ìgbàgbọ́ ti ń ṣiṣẹ́ nípa ìfẹ́.

Ka pipe ipin Gálátíà 5