Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Gálátíà 3:11-18 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

11. Nítorí ó dánilójú pé, a kò dá ẹnìkẹ́ni láre níwájú Ọlọ́run nípa iṣẹ́ òfin: nítorí pé, olódodo yóò yè nípa ìgbàgbọ́.”

12. Òfin kì í sì í ṣe ti ìgbàgbọ́: ṣùgbọ́n “Ẹnikẹ́ni tí ń se wọn yóò yè nípaṣẹ̀ wọn.”

13. Kírísítì ti rà wá padà kúrò lọ́wọ́ ègún òfin, ẹni tí a fi ṣe ègún fún wa: nítorí tí a ti kọ ọ́ pé, “Ìfibú ni olúkúlùkù ẹni tí a fi kọ́ sórí igi.”

14. Kí ìbùkún Ábúráhámù ba à lè wá sórí àwọn aláìkọlà nípa Kírísítì Jésù; kí àwa ba à lè gba ìlérí Ẹ̀mí nípa ìgbàgbọ́.

15. Ará, èmi ń ṣọ̀rọ̀ bí ènìyàn: bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé májẹ̀mú ènìyàn ni, ṣùgbọ́n bí a ti fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀, kò sí ẹni tí ó lè sọ ọ́ di asán, tàbí tí ó lè fi kún un mọ́.

16. Ǹjẹ́ fún Ábúráhámù àti fún irú ọmọ rẹ̀ ni a ti ṣe àwọn ìlérí náà. Òun kò ṣe wí pé, “Àti fún irú-ọmọ rẹ̀,” èyí tí í ṣe Kírísítì.

17. Èyí tí mò ń wí ni pé: Májẹ̀mu tí Ọlọ́run ti fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ níṣáájú, òfin ti ó dé lẹ́yìn ọgbọ̀n-lé-nírinwó ọdún kò lè sọ ọ́ di asán, tí à bá fi mú ìlérí náà di aláìlágbára.

18. Nítorí bí ìjogún náà bá ṣe ti òfin kì í ṣe ti ìlérí mọ́: ṣùgbọ́n Ọlọ́run ti fi í fún Ábúráhámù nípa ìlérí.

Ka pipe ipin Gálátíà 3