Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Gálátíà 1:1-6 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Pọ́ọ̀lù, Àpósítélì tí a rán kì í ṣe láti ọ̀dọ̀ ènìyàn wá, tàbí nípa ènìyàn, ṣùgbọ́n nípa Jésù Kírísítì àti Ọlọ́run Baba, ẹni tí ó jí i dìde kúrò nínú òkú.

2. Àti gbogbo àwọn arákùnrin tí ó wà pẹ̀lú mi,Sí àwọn ìjọ ní Gálátíà:

3. Oore-ọ̀fẹ́ sí yín àti àlàáfíà láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Baba wá àti Jésù Kírísítì Olúwa,

4. ẹni tí ó fí òun tìkararẹ̀ dípò ẹ̀ṣẹ̀ wa, kí ó lè gbà wá kúrò nínú ayé búburú ìsinsin yìí, gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ Ọlọ́run àti Baba wa,

5. ẹni tí ògo wà fún láé àti láéláé. Àmín.

6. Ẹnu yà mi nítorí tí pé ẹ tètè yapa kúrò lọ́dọ̀ ẹni tí ó pè yín sínú oore-ọ̀fẹ́ Kírísítì, sí ìyìn rere mìíràn:

Ka pipe ipin Gálátíà 1