Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àwọn Hébérù 2:15-18 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

15. Kí o sì lè gba gbogbo àwọn tí ó tìtorí ìbẹ̀rù ikú wà lábẹ́ ìdè lọjọ ayé wọn gbogbo kúrò lọ́wọ́ ìbẹ̀rù.

16. Nítorí pé, nítòótọ́, kì í ṣe àwọn ańgẹ́lì ni ó ṣe ìrànlọ́wọ́ fún, ṣùgbọ́n àwọn irú-ọmọ Ábúráhámù ni ó ṣe ìrànlọ́wọ́ fún.

17. Nítorí náà, ó yẹ pé nínú ohun gbogbo kí ó dàbí àwọn ará rẹ̀, kí ó lè jẹ́ aláàánú àti olóòótọ́ Olórí Àlùfáà nínú ohun tí i ṣe ti Ọlọ́run, kí o lè ṣe ètùtù fún ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ènìyàn.

18. Nítorí níwọ̀n bí òun tìkararẹ̀ ti jìyà tí a sì ti dán an wò, òun ní agbára láti ran àwọn tí a ń dánwò lọ́wọ́.

Ka pipe ipin Àwọn Hébérù 2