Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Kọ́ríńtì 8:11-16 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

11. Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ẹ parí ṣíṣe iṣẹ́ náà pẹ̀lú; kí ó baà lè ṣe pé, bí ìmúra tẹ́lẹ̀ fún ṣiṣe ti wà, bẹ́ẹ̀ ni kí ìparí sì wà láti inú agbára yín.

12. Nítorí bí ìmúra tẹ́lẹ̀ bá wà ṣáájú, ó jásí ìtẹ́wọ́gbà gẹ́gẹ́ bí ohun tí ènìyàn bá ní, kì í ṣe gẹ́gẹ́ bí ohun tí kò ní.

13. Nítorí èmi kò fẹ kí àwọn ẹlòmíràn wà ní ìrọ̀rùn, kí ó sì jẹ́ ìpọ́njú fún yín. Ṣùgbọ́n pé nípa mímú dọ́gba,

14. Ní àkókò yìí, pé kí àníṣẹ́kù yín lè ṣe déédé àìní wọn, kí àní ṣẹ́kù tiwọn pẹ̀lú baà lè ṣe déédé àìní yín: kí ìmúdọ́gba baà lè wà.

15. Gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ pé, “Ẹni tí o kó pọ̀ jù, kò ní nǹkan lé tayọ; ẹni tí o kò kéré jù kò ṣe aláìnító.”

16. Ṣùgbọ́n ọpẹ́ ní fún Ọlọ́run ẹni tí ó fi ìtara àníyàn kan náà yìí sí ọkàn Títù fún yín.

Ka pipe ipin 2 Kọ́ríńtì 8