Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Kọ́ríńtì 4:1-6 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Nitorí náà, níwọ̀n bí ó ti jẹ́ pé nípa àánú Ọlọ́run a rí iṣẹ́ ìránṣẹ́ yìí bí àwa ti rí ní iṣẹ́-ìránṣẹ́ yìí, gẹ́gẹ́ bí a ti fi àánú gbà, àárẹ̀ kò mú wá;

2. Ṣùgbọ́n àwa tí kọ gbogbo ohun ìkọ̀kọ̀ tí ó ní ìtìjú sílẹ̀, àwa kò rìn ní ẹ̀tàn, bẹ́ẹ̀ ni àwa kò fi ọwọ́ ẹ̀tàn mú ọ̀rọ̀ Ọlọ́run; ṣùgbọ́n nípa fífí òtítọ́ hàn, àwa ń fí ara wa le ẹ̀rí ọkàn olúkúlùkù ènìyàn lọ́wọ́ níwájú Ọlọ́run.

3. Ṣùgbọ́n báyìí, bí iyinrere wa bá sí farasin, ó farasin fún àwọn tí ó ń ṣègbé.

4. Nínú àwọn ẹni tí Ọlọ́run ayé yìí ti sọ ọkàn àwọn aláìgbàgbọ́ dí afọ́jú, kí ìmọ́lẹ̀ ìyìn rere Kírísítì tí ó lógo, ẹni tí í ṣe àworán Ọlọ́run, má ṣe mọ́lẹ̀ nínú wọn.

5. Nítórí àwa kò wàásù àwa tìkárawa, bí kò se Kírísítì Jésù Olúwa; àwa tikarawa sì jẹ́ ẹrú yín nítorí Jésù.

6. Nítorí Ọlọ́run ni ẹni tí ó wí pé, “Kí ìmọ́lẹ̀ ó mọ́lẹ̀ láti inú òkùnkùn jáde,” òun ní ó ti ń mọ́lẹ̀ lọ́kan wa, láti fún wa ní ìmọ́lẹ̀ ìmọ̀ ògo Ọlọ́run ní ojú Jésù Kírísítì.

Ka pipe ipin 2 Kọ́ríńtì 4